Ṣé látàrí a á sìnlú a à sìnlú yìí náà lọ̀rọ̀ wá di fàá ká já a báyìí, tí àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú ń jùkò ọ̀rọ̀ lu ra wọn.
Nífèsì padà sí n tí aṣíwájú Tinubu ṣọ , ẹgbẹ́ òṣèlú “Peoples Democratic Party,PDP ” náà tí fèsì padà fún Aṣíwájú Bola Ahmed Tinubu lórí fídíò tó ti ní kí àwọn èèyàn Edo má ṣe dìbò fún Godwin Obaseki.
Gómìnà Godwin Obaseki ni olùdíje ẹgbẹ́ náà nínú ìdìbò Gómìnà tó ń bọ̀ lọ́nà.
Nínú àtẹjáde tí ẹgbẹ́ náà fi síta lójú òpó abẹ́yefò Twitter, wọ́n ní ẹ̀yìnkùlé baba Tinubu kò dé Edo, nítorí náà gàlègàlè rẹ̀ tó ń ṣe nínú fídíò ọ̀hún kò le è yí ìpinnu àwọn ará ìlú Edo padà.
Ẹgbẹ́ náà sọ pé àwọn èèyàn Edo ti pinu lọ́kàn wọn ti pẹ́ láti yan Obaseki sí ipò padà nítorí náà kí Tinubu lọ ṣa gbé jẹ́ ẹ́ mọ́wọ́.
Yàtọ̀ sí ọ̀rọ̀ ẹgbẹ́ yìí, Olùdámọ̀ràn Gómìnà Obaseki lórí ọ̀rọ̀ ìròyìn, Crusoe Osagie sọ pé kí Tinubu dá ọ̀rọ̀ rẹ̀ padà.
Ó ṣàlàyé pé àwọn èèyàn Edo kò fààyè gba baba ìsàlẹ̀ nínú òṣèlú ìpínlẹ̀ wọn nítorí náà kí Tinubu fàwọn lọ́rùn sílẹ̀.
Fẹ́mi Akínṣọlá
Èèkàn ẹgbẹ́ òṣèlú APC nípìńlẹ̀ Èkó, Lanre Razak ti jáde láyé lẹ́ni ọdún mẹ́rìnléláàdọ́rin.
Kí ikú ó pajú èèyàn dé lójijì ti wá fẹ́ ẹ̀ kúrò ní ń tí wọ́n kíìyàn yàn pé Ọlọ́run má jẹ́ á rírú ẹ̀ mọ́, bí ó se pé ká sá maa sọ fún Ọlọ́run pé kọ́dún ó jìnà síra wọn.
Ìṣẹ́jú ìṣẹ́jú sáà ni ẹ̀mí ń bọ́ lára gbogbo n tí Aláwùràbí dá, tèèyàn ló kàn wá jù ,la ṣe ń gbarata.
Ọkàn pàtàkì tún ni ti
Ọ̀gbẹ́ni Lanre Razak yìí tó papòdà lọ́jọ́ Àbámẹ́ta ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kẹjọ ọdún 2020 yìí ,lẹ́yìn àìsàn ráńpẹ́.
Nígbà ayé rẹ̀, Ọ̀gbẹ́ni Razak wà nínú Ìgbìmọ̀ tó ń gba Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó lámọ̀ràn.
Ọ̀gbẹ́ni Rasak kọ́kọ́ fi èròńgbà rẹ̀ hàn láti díje fún ipò Sẹ́nétọ̀í lẹ́kùn ìlà oòrùn ìpínlẹ̀ Èkó kí ó tó yọwọ́ níbẹ̀ ṣaájú ìbò abẹ́lé.
Ọjọ́ Àìkú ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kẹjọ yìí ni wọn yóó ṣin Ọ̀gbẹ́ni Rasak ní Ìlànà ẹ̀ṣìn mùsùlùmí.
Fẹ́mi Akínṣọlá
]]>Ogbeni Ramoni Igbalode Abbas to je omo Naijiria ti owo te ni ilu Dubai pelu esun jibiti lilu lori ero ayelujara lose to koja ni egbe oselu APC ni owo PDP ko mo nibe.
Gege bi atejade to egbe oselu APC gbe jade nipa irinkurin egbe oselu PDP paapaa julo ni asiko idibo odun 2019 to koja. APC ni ki won to so pere, won ti ko ara won lo Dubai fun ipade.
APC ni iru ipade wo ni won n lo se ni orileede naa ti ko see se ni Naijiria. APC tun ni gbogbo foto ti won ya pelu Hushpuppi nibi ipade ati gbogbo ohun to da won po lo maa jade laipe.
APC ni o da awon.loju to ada pe awon oyinbo maa wadii gbogbo irinajo Ogbeni afunrasi naa.
Gege bi atejade egbe APC ti igbakeji akole agba egbe naaogbeni Yekini Nabena fowl si, APC ni ki egbe PDP maa se sun asunpiye nitori ejo naa ti kuro ni Dubai lo si Chicago ni orileede Amerika. O ni afaimo ki Ogbeni Hushpuppi ma se fi ewon ogun odun gbara.
]]>Ó dà bíi pé , ẹ kú àtilé bọ́ọ́lé ló kù báyìí, tí àwa òlùdìbò yóó ma kí àwọn olóṣèlú wọ̀nyí lásìkò yìí, tí wọ́n kàn ń múwa ṣeré nínú ọpọlọ, yí bìrìpé láti inú ẹgbẹ́ kan sí ìkejì.
Ìròyìn mí-ìn tí a gbọ́ báyìí ni pé ìgbákejì Gómìnà ìpínlẹ̀ Òǹdó, Agboola Ajayi ti fẹgbẹ́ òṣèlú APC sílẹ̀ bọ́ sẹ́gbẹ́ PDP.
Akọ̀wé Ìròyìn fún Ọ̀gbẹ́ni Ajayi, Tope Okeowo ló fìdí ọ̀rọ̀ náà múlẹ̀.
Okeowo ṣọ fún akọ̀ròyìn pé lọ́jọ́ Àìkú ni ìgbákejì Gómìnà Òǹdó kọ̀wé fipò sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú APC.
Tijó ti ìlù ni àwọnn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP fi kí Ọ̀gbẹ́ni Ajayi káàbọ̀ sínú ẹgbẹ́ wọn.
Kó dà, àwọn èèkàn nínú ẹgbẹ́ PDP gbàdúrà fún un bí wọ́n ti fi káàdì ọmọ ẹgbẹ́ lé e lọ́wọ́.
Ẹ̀wẹ̀, Akọ̀wé Ìròyìn rẹ̀ sọ fún akọròyìn pé lọjọ Ajé ni Ọ̀gbẹ́ni Ajayi yóó báwọn akọ̀ròyìn ṣọ̀rọ̀ lórí ìdí tó fi kúrò nínú ẹgbẹ́ APC lọ sí PDP àti ìgbésẹ̀ tó kan fún un láti gbé.
Fẹ́mi Akínṣọlá
]]>Àwọn àgbà bọ̀ wọ́n ní bí ọ̀rọ̀ ńlá kò bá tí ì tán, èèyàn ńlá kò níí sinmi àròyé.
Sinimọ́ oríta sì ń tẹ̀síwájú pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tó jẹ mọ́ yíyàn ọmọ oyè nínú ẹgbẹ́ òṣèlú náà.
Ìròyìn míì tó jọ eré oníṣẹ ti ń fi yé ni pé, ìgbákejì Akọ̀wé àpapọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú APC, Victor Giadom ti bọ́ s’órí oyè gẹ́gẹ́ bíi adelé Alága àpapọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú náà.
Ọ̀rọ̀ ti di iṣu ata yán-an-yàn-an lẹ́gbẹ́ òṣèlú APC báyìí pẹ̀lú bí ẹgbẹ́ òṣèlú ọ̀hún ṣe ń ní adelé Alága àpapọ̀ méjì láàrin wákàtí díẹ̀ sí ara wọn.
Ní kété tí ilé ẹjọ́ pàṣẹ kí Adams Oshiomole ó fi ipò sílẹ̀, ni ẹgbẹ́ òṣèlú APC ti kéde Sẹ́nétọ̀ Abíọ́lá Ajímọ̀bi gẹ́gẹ́ bí adelé Alága àpapọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú náà.
Àmọ́ ṣá, kò pẹ́ púpọ̀ ni ẹni tó jẹ́ ìgbákejì Akọ̀wé àgbà ẹgbẹ́ òṣèlú ọ̀hún, Victor Giadom jáde sí bọnbọ pẹ̀lú ìwé ìdájọ́ láti Ilé ẹjọ́ kan , eléyìí tó ní òun ni ó tọ́ sí láti di ipò náà mú.
Ní Ọjọ́rú sì ni Gaidom gun orí àga náà gẹ́gẹ́ bí adelé Alága àpapọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú APC.
Ní wàràǹsesà tí ó wọlé ni ó ti kéde pé òun ń gba àkóso ní ìbámu pẹ̀lú ìdájọ́ Ilé ẹjọ́ tó ní ó fún òun lágbára àti ṣe bẹ́ẹ̀.
Bákan náà ló wọ́gilé ètò àyẹ̀wò àwọn olùdíje fún ipò gómìnà lábẹ́ àṣìá ẹgbẹ́ òṣèlú APC ní Ìpínlẹ̀ Edo.
Ó fi kún un pé gbá-gbá gbá làwọn ọmọ ìgbìmọ̀ májẹ̀óbàjẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú náà wà lẹ́yìn òun lórí ìgbésẹ̀ náà.
Kò sí àníànì, ọ̀rọ̀ yìí kò le parí síbẹ̀, bí ó bá se ń lọ, a o máa jábọ̀ fún un yín.
Fẹ́mi Akínṣọlá
Lati owo Hamzat Mujeeb Olawale
Awon omo ile igbimo asofin agba l’Abuja ti won je ti omo egbe APC ti tako aba eleyii to wa nibamu pelu ileri ti Aare se lati maa san egberun marun-un owo naira (5K) fun awon odo ti ko nise lowo. Ileri yii ni aare se nigba eto iponlongo ibo. Sugbon bayii, awon omo ile igbimo asofin ti won je omo egbe APC ti da aba naa nu bi omi isanwo.
]]>